Ìfihàn 8:12
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
12 Angẹli kẹrin sì fún ìpè tirẹ̀, a sì kọlu ìdámẹ́ta oòrùn, àti ìdámẹ́ta òṣùpá, àti ìdámẹ́ta àwọn ìràwọ̀, ki ìdámẹ́ta wọn lè ṣókùnkùn, kí ọjọ́ má ṣe mọ́lẹ̀ fún ìdámẹ́ta rẹ̀, àti òru bákan náà.
Read full chapter
Isaiah 13:10
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
10 (A)Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti ìkójọpọ̀ wọn
kò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn.
Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn yóò di òkùnkùn
àti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.
Esekiẹli 32:7
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
7 Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run dé
àwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn;
èmi yóò sì fi ìkùùkuu bo oòrùn
òṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀
Joẹli 2:10-11
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
10 (A)Ayé yóò mì níwájú wọn;
àwọn ọ̀run yóò wárìrì;
oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn,
àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
11 (B)Olúwa yóò sì bú ramúramù
jáde níwájú ogun rẹ̀:
nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi;
nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ;
nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi;
ara ta ni ó lè gbà á?
Sefaniah 1:15
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
15 Ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú,
ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú,
ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro
ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba,
ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.