Add parallel Print Page Options

Ọkàn tí o bá sẹ̀ ni yóò kú

18 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé: (A)“Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé:

“ ‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan,
    eyín àwọn ọmọ sì kan.’

“Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli. (B)Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.

“Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà,
    tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ
tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga,
    tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli,
ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
    tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.
Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára,
    ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀
gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un,
    kò fi ipá jalè
ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ,
    tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.
Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá,
    tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù.
Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀,
    ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.
Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi,
    tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo.
Ó jẹ́ olódodo,
    yóò yè nítòótọ́,
    Olúwa Olódùmarè wí.

10 “Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀ 11 (tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì):

“Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga,
tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.
12 Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára,
ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí,
o gbójú sókè sí òrìṣà,
ó sì ń ṣe ohun ìríra.
13 Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù.

Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.

14 “Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:

15 “Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga
    tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli,
tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
16 tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára,
    tí kò dá ohun ògo dúró
tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè
    ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ,
    tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.
17 Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀,
    kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù,
tí ó ń pa òfin mi mọ́,
    tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi.

Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè! 18 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.

19 “Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè. 20 Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.

21 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú. 22 A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè 23 Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?

24 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.

25 “Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pe, ‘ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí ìwọ ilé Israẹli: ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún? 26 Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá. 27 Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là. 28 Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú 29 Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?

30 “Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín. 31 (C)Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli? 32 (D)Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!

The One Who Sins Will Die

18 The word of the Lord came to me: “What do you people mean by quoting this proverb about the land of Israel:

“‘The parents eat sour grapes,
    and the children’s teeth are set on edge’?(A)

“As surely as I live, declares the Sovereign Lord, you will no longer quote this proverb(B) in Israel. For everyone belongs to me, the parent as well as the child—both alike belong to me. The one who sins(C) is the one who will die.(D)

“Suppose there is a righteous man
    who does what is just and right.
He does not eat at the mountain(E) shrines
    or look to the idols(F) of Israel.
He does not defile his neighbor’s wife
    or have sexual relations with a woman during her period.(G)
He does not oppress(H) anyone,
    but returns what he took in pledge(I) for a loan.
He does not commit robbery(J)
    but gives his food to the hungry(K)
    and provides clothing for the naked.(L)
He does not lend to them at interest
    or take a profit from them.(M)
He withholds his hand from doing wrong
    and judges fairly(N) between two parties.
He follows my decrees(O)
    and faithfully keeps my laws.
That man is righteous;(P)
    he will surely live,(Q)
declares the Sovereign Lord.

10 “Suppose he has a violent son, who sheds blood(R) or does any of these other things[a] 11 (though the father has done none of them):

“He eats at the mountain shrines.(S)
He defiles his neighbor’s wife.
12 He oppresses the poor(T) and needy.
He commits robbery.
He does not return what he took in pledge.(U)
He looks to the idols.
He does detestable things.(V)
13 He lends at interest and takes a profit.(W)

Will such a man live? He will not! Because he has done all these detestable things, he is to be put to death; his blood will be on his own head.(X)

14 “But suppose this son has a son who sees all the sins his father commits, and though he sees them, he does not do such things:(Y)

15 “He does not eat at the mountain shrines(Z)
    or look to the idols(AA) of Israel.
He does not defile his neighbor’s wife.
16 He does not oppress anyone
    or require a pledge for a loan.
He does not commit robbery
    but gives his food to the hungry(AB)
    and provides clothing for the naked.(AC)
17 He withholds his hand from mistreating the poor
    and takes no interest or profit from them.
He keeps my laws(AD) and follows my decrees.

He will not die for his father’s sin; he will surely live. 18 But his father will die for his own sin, because he practiced extortion, robbed his brother and did what was wrong among his people.

19 “Yet you ask, ‘Why does the son not share the guilt of his father?’ Since the son has done what is just and right and has been careful to keep all my decrees, he will surely live.(AE) 20 The one who sins is the one who will die.(AF) The child will not share the guilt of the parent, nor will the parent share the guilt of the child. The righteousness of the righteous will be credited to them, and the wickedness of the wicked will be charged against them.(AG)

21 “But if(AH) a wicked person turns away from all the sins they have committed and keeps all my decrees(AI) and does what is just and right, that person will surely live; they will not die.(AJ) 22 None of the offenses they have committed will be remembered against them. Because of the righteous things they have done, they will live.(AK) 23 Do I take any pleasure in the death of the wicked? declares the Sovereign Lord. Rather, am I not pleased(AL) when they turn from their ways and live?(AM)

24 “But if a righteous person turns(AN) from their righteousness and commits sin and does the same detestable things the wicked person does, will they live? None of the righteous things that person has done will be remembered. Because of the unfaithfulness(AO) they are guilty of and because of the sins they have committed, they will die.(AP)

25 “Yet you say, ‘The way of the Lord is not just.’(AQ) Hear, you Israelites: Is my way unjust?(AR) Is it not your ways that are unjust? 26 If a righteous person turns from their righteousness and commits sin, they will die for it; because of the sin they have committed they will die. 27 But if a wicked person turns away from the wickedness they have committed and does what is just and right, they will save their life.(AS) 28 Because they consider all the offenses they have committed and turn away from them, that person will surely live; they will not die.(AT) 29 Yet the Israelites say, ‘The way of the Lord is not just.’ Are my ways unjust, people of Israel? Is it not your ways that are unjust?

30 “Therefore, you Israelites, I will judge each of you according to your own ways, declares the Sovereign Lord. Repent!(AU) Turn away from all your offenses; then sin will not be your downfall.(AV) 31 Rid(AW) yourselves of all the offenses you have committed, and get a new heart(AX) and a new spirit. Why(AY) will you die, people of Israel?(AZ) 32 For I take no pleasure in the death of anyone, declares the Sovereign Lord. Repent(BA) and live!(BB)

Footnotes

  1. Ezekiel 18:10 Or things to a brother