Add parallel Print Page Options

Ìpohùnréré ẹkún fún Farao

32 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kejìlá, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá: “Ọmọ ènìyàn, ṣe ìpohùnréré ẹkún nítorí Farao ọba Ejibiti kí o sì wí fún un:

“ ‘Ìwọ dàbí kìnnìún láàrín àwọn
    orílẹ̀-èdè náà;
ìwọ dàbí ohun ẹ̀mí búburú inú àwọn omi okun to ń lọ
    káàkiri inú àwọn odò rẹ,
ìwọ fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ omi
    láti mú kí àwọn odò ní ẹrẹ̀.

“ ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí:

“ ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ìpéjọ ènìyàn
    èmi yóò da àwọ̀n mi bò ọ́
    wọn yóò sì fà ọ́ sókè nínú àwọ̀n mi.
Èmi yóò jù ọ́ sí orí ilẹ̀
    èmi yóò sì fà ọ́ sókè sí orí pápá gbangba.
Èmi yóò jẹ́ kí gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe
    àtìpó ní orí rẹ.
Gbogbo àwọn ẹranko ayé yóò fi
    ìwọra gbé ara wọn lórí rẹ.
Èmi yóò tan ẹran-ara rẹ ká sórí
    àwọn òkè gíga
ìyókù ara rẹ ní wọn yóò fi kún
    àwọn àárín àwọn òkè gíga
Ẹ̀jẹ̀ rẹ ti ń sàn ní èmi yóò sì fi rin ilẹ̀ náà
    gbogbo ọ̀nà sí orí àwọn òkè gíga,
    àwọn àlàfo jíjìn ní wọn yóò kún fún ẹran-ara rẹ.
Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run dé
    àwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn;
èmi yóò sì fi ìkùùkuu bo oòrùn
    òṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀
Gbogbo ìmọ́lẹ̀ títàn ní ojú ọ̀run
    ni èmi yóò mú ṣókùnkùn lórí rẹ;
èmi yóò mú òkùnkùn wá sórí ilẹ̀ rẹ,
    ni Olúwa Olódùmarè wí
Èmi yóò da ọkàn ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn rú
    nígbà tí mo bá mú ìparun rẹ wá
ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ
    kò í tí ì mọ̀.
10 Èmi yóò mú kí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn dẹ́rùbà ọ́,
    àwọn ọba wọn yóò sì wárìrì fún
ìbẹ̀rù pẹ̀lú ìpayà nítorí rẹ,
    nígbà tí mo bá ju idà mi ní iwájú wọn
Ní ọjọ́ ìṣubú rẹ
    ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú wọn yóò wárìrì
    ní gbogbo ìgbà fún ẹ̀mí rẹ.

11 “ ‘Nítorí èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí:

“ ‘Idà ọba Babeli
    yóò wá sí orí rẹ,
12 Èmi yóò mú kí ìjọ ènìyàn rẹ kí ó
    tí ipa idà àwọn alágbára ènìyàn ṣubú
àwọn orílẹ̀-èdè aláìláàánú jùlọ.
    Wọn yóò tú ìgbéraga Ejibiti ká,
    gbogbo ìjọ rẹ ní a yóò dá ojú wọn bolẹ̀.
13 Gbogbo ẹran ọ̀sìn rẹ ni èmi yóò parun
    ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi
kì i ṣe ẹsẹ̀ ènìyàn ní yóò tẹ ibẹ̀
    ẹsẹ̀ ẹran ọ̀sìn kì yóò sì mú kí ibẹ̀ ni ẹrọ̀fọ̀.
14 Lẹ́yìn náà èmi yóò mú kí omi rẹ̀ tòrò
    kí àwọn odò rẹ̀ kí o sàn bí epo,
    ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 Nígbà tí mo bá sọ Ejibiti di ahoro,
    tí mo sì kó gbogbo ohun tí ó wà ní orí ilẹ̀ náà kúrò.
Nígbà tí mo bá gé àwọn olùgbé ibẹ̀ lulẹ̀,
    nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’

16 “Èyí yìí ni ẹkún tí a yóò sun fún un. Àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè yóò sun ún; nítorí Ejibiti àti gbogbo ìjọ rẹ, wọn yóò sun ún, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

17 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mí wá: 18 “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún lórí Ejibiti kí o sì ránṣẹ́ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ àti òun àti àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè alágbára, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ìsàlẹ̀, kòtò. 19 Sọ fún wọn, ‘Ǹjẹ́ ìwọ ní ojúrere jù àwọn tí o kù lọ? Lọ sí ìsàlẹ̀ kí a sì tẹ́ ọ sí àárín àwọn aláìkọlà náà.’ 20 Wọn yóò ṣubú láàrín àwọn tí a fi idà pa. A fa idà yọ; jẹ́ kí a wọ́ Ejibiti kúrò pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀. 21 Láti inú isà òkú alágbára tí í ṣe aṣáájú yóò sọ nípa Ejibiti àti àwọn àlejò rẹ̀, ‘Wọn ti wá sí ìsàlẹ̀, wọn sì sùn pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.’

22 “Asiria wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo jagunjagun rẹ̀; àwọn isà òkú àwọn tí a ti pa sì yí i ká, gbogbo àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú. 23 Isà òkú wọn wà ní ibi tí ó jinlẹ̀ gan an nínú kòtò. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè ní a pa, tí ó ti ipa idà ṣubú.

24 “Elamu wà níbẹ̀, o yí isà òkú rẹ̀ ká pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀. Gbogbo wọn ni a pa, àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè lọ sí ìsàlẹ̀ láìkọlà sí abẹ́ ilẹ̀. Wọ́n gba ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò. 25 A ṣe ibùsùn fún un láàrín àwọn tí a pa, pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀ tí ó yí isà òkú ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, tí a fi idà pa. Nítorí pé a tan ẹ̀rù wọn ká ilẹ̀ alààyè, wọn ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò; a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a pa.

26 “Meṣeki àti Tubali wà níbẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ogun wọn yí isà òkú wọn ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, wọ́n fi idà pa wọ́n nítorí ẹ̀rù tiwọn tàn ká ilẹ̀ alààyè. 27 Wọn kì yóò sì dùbúlẹ̀ ti àwọn tí ó ṣubú nínú àwọn aláìkọlà, tí wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun wọn, wọ́n tí fi idà wọn rọ orí wọn. Ṣùgbọ́n àìṣedéédéé wọn yóò wà ní orí egungun wọn—bí wọ́n tilẹ̀ jẹ́ ẹ̀rù àwọn alágbára ní ilẹ̀ alààyè.

28 “Ìwọ náà, Farao, ní yóò ṣẹ, ti yóò dùbúlẹ̀ láàrín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.

29 “Edomu wà níbẹ̀, àwọn ọba rẹ̀ àti gbogbo ọmọbìnrin ọba; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní agbára, a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. Wọn dùbúlẹ̀ pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn ti o lọ sínú kòtò.

30 “Gbogbo àwọn ọmọ-aládé ilẹ̀ àríwá àti gbogbo àwọn ará Sidoni wà níbẹ̀; wọn lọ sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí a pa ní ìtìjú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ṣe okùnfà ẹ̀rù pẹ̀lú agbára wọn. Wọn sùn ní àìkọlà pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa, wọn sì ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.

31 “Farao, òun àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ yóò rí wọn, a yóò sì tù ú nínú nítorí gbogbo ogun rẹ̀ tí a fi idà pa, ní Olúwa Olódùmarè wí. 32 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè, Farao àti gbogbo ogun rẹ̀ ni a yóò tẹ́ sí àárín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa ní Olúwa Olódùmarè wí.”

A Lament Over Pharaoh

32 In the twelfth year, in the twelfth month on the first day, the word of the Lord came to me:(A) “Son of man, take up a lament(B) concerning Pharaoh king of Egypt and say to him:

“‘You are like a lion(C) among the nations;
    you are like a monster(D) in the seas(E)
thrashing about in your streams,
    churning the water with your feet
    and muddying the streams.(F)

“‘This is what the Sovereign Lord says:

“‘With a great throng of people
    I will cast my net over you,
    and they will haul you up in my net.(G)
I will throw you on the land
    and hurl you on the open field.
I will let all the birds of the sky settle on you
    and all the animals of the wild gorge themselves on you.(H)
I will spread your flesh on the mountains
    and fill the valleys(I) with your remains.
I will drench the land with your flowing blood(J)
    all the way to the mountains,
    and the ravines will be filled with your flesh.(K)
When I snuff you out, I will cover the heavens
    and darken their stars;
I will cover the sun with a cloud,
    and the moon will not give its light.(L)
All the shining lights in the heavens
    I will darken(M) over you;
    I will bring darkness over your land,(N)
declares the Sovereign Lord.
I will trouble the hearts of many peoples
    when I bring about your destruction among the nations,
    among[a] lands you have not known.
10 I will cause many peoples to be appalled at you,
    and their kings will shudder with horror because of you
    when I brandish my sword(O) before them.
On the day(P) of your downfall
    each of them will tremble
    every moment for his life.(Q)

11 “‘For this is what the Sovereign Lord says:

“‘The sword(R) of the king of Babylon(S)
    will come against you.(T)
12 I will cause your hordes to fall
    by the swords of mighty men—
    the most ruthless of all nations.(U)
They will shatter the pride of Egypt,
    and all her hordes will be overthrown.(V)
13 I will destroy all her cattle
    from beside abundant waters
no longer to be stirred by the foot of man
    or muddied by the hooves of cattle.(W)
14 Then I will let her waters settle
    and make her streams flow like oil,
declares the Sovereign Lord.
15 When I make Egypt desolate
    and strip the land of everything in it,
when I strike down all who live there,
    then they will know that I am the Lord.(X)

16 “This is the lament(Y) they will chant for her. The daughters of the nations will chant it; for Egypt and all her hordes they will chant it, declares the Sovereign Lord.”

Egypt’s Descent Into the Realm of the Dead

17 In the twelfth year, on the fifteenth day of the month, the word of the Lord came to me:(Z) 18 “Son of man, wail for the hordes of Egypt and consign(AA) to the earth below both her and the daughters of mighty nations, along with those who go down to the pit.(AB) 19 Say to them, ‘Are you more favored than others? Go down and be laid among the uncircumcised.’(AC) 20 They will fall among those killed by the sword. The sword is drawn; let her be dragged(AD) off with all her hordes.(AE) 21 From within the realm of the dead(AF) the mighty leaders will say of Egypt and her allies, ‘They have come down and they lie with the uncircumcised,(AG) with those killed by the sword.’

22 “Assyria is there with her whole army; she is surrounded by the graves of all her slain, all who have fallen by the sword. 23 Their graves are in the depths of the pit(AH) and her army lies around her grave.(AI) All who had spread terror in the land of the living are slain, fallen by the sword.

24 “Elam(AJ) is there, with all her hordes around her grave. All of them are slain, fallen by the sword.(AK) All who had spread terror in the land of the living(AL) went down uncircumcised to the earth below. They bear their shame with those who go down to the pit.(AM) 25 A bed is made for her among the slain, with all her hordes around her grave. All of them are uncircumcised,(AN) killed by the sword. Because their terror had spread in the land of the living, they bear their shame with those who go down to the pit; they are laid among the slain.

26 “Meshek and Tubal(AO) are there, with all their hordes around their graves. All of them are uncircumcised, killed by the sword because they spread their terror in the land of the living. 27 But they do not lie with the fallen warriors of old,[b](AP) who went down to the realm of the dead with their weapons of war—their swords placed under their heads and their shields[c] resting on their bones—though these warriors also had terrorized the land of the living.

28 “You too, Pharaoh, will be broken and will lie among the uncircumcised, with those killed by the sword.

29 “Edom(AQ) is there, her kings and all her princes; despite their power, they are laid with those killed by the sword. They lie with the uncircumcised, with those who go down to the pit.(AR)

30 “All the princes of the north(AS) and all the Sidonians(AT) are there; they went down with the slain in disgrace despite the terror caused by their power. They lie uncircumcised(AU) with those killed by the sword and bear their shame with those who go down to the pit.(AV)

31 “Pharaoh—he and all his army—will see them and he will be consoled(AW) for all his hordes that were killed by the sword, declares the Sovereign Lord. 32 Although I had him spread terror in the land of the living, Pharaoh(AX) and all his hordes will be laid among the uncircumcised, with those killed by the sword, declares the Sovereign Lord.”(AY)

Footnotes

  1. Ezekiel 32:9 Hebrew; Septuagint bring you into captivity among the nations, / to
  2. Ezekiel 32:27 Septuagint; Hebrew warriors who were uncircumcised
  3. Ezekiel 32:27 Probable reading of the original Hebrew text; Masoretic Text punishment