Add parallel Print Page Options

Kò sí ìgbẹ́kẹ̀lé ẹlẹ́ran ara

Ní àkótán ará, ẹ máa yọ̀ nínú Olúwa wa. Kì í ṣe ìnira fún mi láti kọ̀wé ohun kan náà sí yín, ṣùgbọ́n fún yín ó jẹ́ ohun ààbò. Ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn ajá, ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn oníṣẹ́ búburú, ẹ sì kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn onílà. (A)Nítorí àwa ni onílà, tí ń sin Ọlọ́run nípa ti Ẹ̀mí, àwa sì ń ṣògo nínú Kristi Jesu, àwa kò sí ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ẹran-ara. (B)Bí èmi tìkára mi pẹ̀lú ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara.

Bí ẹnikẹ́ni bá rò pé òun ni ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara, tèmi tilẹ̀ pọ̀: Ẹni tí a kọ nílà ní ọjọ́ kẹjọ, láti inú kùkùté Israẹli wá, láti inú ẹ̀yà Benjamini, Heberu láti inú Heberu wá; nítorí, ní ti òfin Farisi ni èmi; Ní ti ìtara, èmi ń ṣe inúnibíni sí ìjọ; ní ti òdodo tí ó wà nínú òfin, mo jẹ́ aláìlẹ́gàn.

Ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó ti jásí èrè fún mi, àwọn ni mo ti kà sí òfo nítorí Kristi. Nítòótọ́ láìṣe àní àní mo sì ka ohun gbogbo sí òfo nítorí ìtayọ ìmọ̀ Kristi Jesu Olúwa mi; nítorí ẹni ti mo ti ṣòfò ohun gbogbo, mo si kà wọn sí ohun tí kò ní èrè, kí èmi lè jèrè Kristi, Kí a sì lè bá mi nínú rẹ̀, láìní òdodo tí èmi tìkára mi, tí ó ti inú òfin wá, ṣùgbọ́n èyí tí ó ti inú ìgbàgbọ́ wá nínú Kristi, òdodo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run nípasẹ̀ ìgbàgbọ́; 10 Èmi mọ̀ ọ́n, àti agbára àjíǹde rẹ̀, àti láti jẹ́ alábápín nínú ìyà rẹ̀ nígbà tí mo bá fi ara mọ́ ọn nínú ikú rẹ̀; 11 nípasẹ̀ bẹ́ẹ̀ kí èmi lè ní àjíǹde kúrò nínú òkú.

12 Kì í ṣe pé ọwọ́ mi ti tẹ̀ ẹ́ ná, tàbí mo ti di pípé: ṣùgbọ́n èmi ń lépa sí i, bí ọwọ́ mi yóò lè tẹ èrè náà nítorí èyí tí a ti dì mímú pẹ̀lú, láti ọ̀dọ̀ Kristi Jesu wá. 13 Ará, èmi kò kara mi sí ẹni ti ọwọ́ rẹ̀ ti tẹ̀ ẹ́ ná: Ṣùgbọ́n ohun kan yìí ni èmi ń ṣe, èmi ń gbàgbé àwọn nǹkan tí ó ti kọjá. Lẹ́yìn náà mo ń nàgà wo àwọn nǹkan tí ó wà níwájú. 14 Èmi ń lépa láti dé òpin eré ìje náà fún èrè ìpè gíga Ọlọ́run nínú Kristi Jesu.

15 Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí àwa tí a dàgbà nípa ti ẹ̀mí ni èrò yìí; bí ẹ̀yin bá sì ní èrò mìíràn nínú ohunkóhun, èyí náà pẹ̀lú ni Ọlọ́run yóò fihàn yín. 16 Kìkì pé, ki a ma gbe ìgbé ayé gẹ́gẹ́ bi èyí ti a ri gba.

17 (C)Ará, ẹ jùmọ̀ ṣe àfarawé mi, ẹ ṣe àkíyèsí àwọn tí ń rìn bẹ́ẹ̀, àní bí ẹ ti ní wa fún àpẹẹrẹ. 18 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní ń rìn, nípasẹ̀ àwọn ẹni tí mo ti ń wí fún yín nígbàkúgbà, àní, tí mo sì ń sọkún bí mo ti ń wí fún yín nísinsin yìí, pé, ọ̀tá àgbélébùú Kristi ni wọ́n: 19 Ìgbẹ̀yìn wọn ni ìparun, ikùn wọn sì ni Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń ṣògo nínú ìtìjú wọn, àwọn ẹni tí ń tọ́jú ohun ti ayé. 20 Nítorí ìlú ìbílẹ̀ wá ń bẹ̀ ní ọ̀run: láti ibi ti àwa pẹ̀lú gbé ń fojúsọ́nà fún Olùgbàlà, Jesu Kristi Olúwa. 21 (D)Ẹni tí yóò sọ ara ìrẹ̀lẹ̀ wa di ọ̀tún kí ó lè bá ara ògo rẹ̀ mu, nípa agbára tí ó mú kí ó ṣe é ṣe fún un láti tẹ orí ohun gbogbo bá fún ara rẹ̀.

No Confidence in the Flesh

Further, my brothers and sisters, rejoice in the Lord! It is no trouble for me to write the same things to you again,(A) and it is a safeguard for you. Watch out for those dogs,(B) those evildoers, those mutilators of the flesh. For it is we who are the circumcision,(C) we who serve God by his Spirit, who boast in Christ Jesus,(D) and who put no confidence in the flesh— though I myself have reasons for such confidence.(E)

If someone else thinks they have reasons to put confidence in the flesh, I have more: circumcised(F) on the eighth day, of the people of Israel,(G) of the tribe of Benjamin,(H) a Hebrew of Hebrews; in regard to the law, a Pharisee;(I) as for zeal,(J) persecuting the church;(K) as for righteousness based on the law,(L) faultless.

But whatever were gains to me I now consider loss(M) for the sake of Christ. What is more, I consider everything a loss because of the surpassing worth of knowing(N) Christ Jesus my Lord, for whose sake I have lost all things. I consider them garbage, that I may gain Christ(O) and be found in him, not having a righteousness of my own that comes from the law,(P) but that which is through faith in[a] Christ—the righteousness(Q) that comes from God on the basis of faith.(R) 10 I want to know(S) Christ—yes, to know the power of his resurrection and participation in his sufferings,(T) becoming like him in his death,(U) 11 and so, somehow, attaining to the resurrection(V) from the dead.

12 Not that I have already obtained all this, or have already arrived at my goal,(W) but I press on to take hold(X) of that for which Christ Jesus took hold of me.(Y) 13 Brothers and sisters, I do not consider myself yet to have taken hold of it. But one thing I do: Forgetting what is behind(Z) and straining toward what is ahead, 14 I press on(AA) toward the goal to win the prize(AB) for which God has called(AC) me heavenward in Christ Jesus.

Following Paul’s Example

15 All of us, then, who are mature(AD) should take such a view of things.(AE) And if on some point you think differently, that too God will make clear to you.(AF) 16 Only let us live up to what we have already attained.

17 Join together in following my example,(AG) brothers and sisters, and just as you have us as a model, keep your eyes on those who live as we do.(AH) 18 For, as I have often told you before and now tell you again even with tears,(AI) many live as enemies of the cross of Christ.(AJ) 19 Their destiny(AK) is destruction, their god is their stomach,(AL) and their glory is in their shame.(AM) Their mind is set on earthly things.(AN) 20 But our citizenship(AO) is in heaven.(AP) And we eagerly await a Savior from there, the Lord Jesus Christ,(AQ) 21 who, by the power(AR) that enables him to bring everything under his control, will transform our lowly bodies(AS) so that they will be like his glorious body.(AT)

Footnotes

  1. Philippians 3:9 Or through the faithfulness of