Add parallel Print Page Options

15 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ! (A)Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí:

“ ‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú;
àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà;
àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn;
àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’

“Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun. N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.

“Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu?
    Ta ni yóò dárò rẹ?
    Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa
    “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn.
Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run;
    Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ,
    Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà.
Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun
    bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn
    kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju
    yanrìn Òkun lọ.
Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun
    kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn.
    Lójijì ni èmi yóò mú
    ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò
    sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ
yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò
    di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi
yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú
    àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,”
    ni Olúwa wí.

10 Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi:
    ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà,
èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni
    síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.

11 Olúwa sọ pé,

“Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó.
    Dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ
    tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.

12 “Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin
    irin láti àríwá tàbí idẹ?

13 “Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ
    ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba
nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ
    jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
14 Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ
    ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú
    mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”

15 Ó yé ọ, ìwọ Olúwa rántí mi kí o
    sì ṣe ìtọ́jú mi; gbẹ̀san mi lára
àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún
    ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ, nínú bí
    mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
16 Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n
    Àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi
Nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí
    Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
17 Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn.
    N ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀;
mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà
    lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
18 Èéṣe tí ìrora mi kò lópin,
    tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn?
Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi,
    gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?

19 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí:

“Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà
    wá kí o lè máa sìn mí. Tí ó bá
sọ ọ̀rọ̀ tó dára ìwọ yóò di agbẹnusọ
    mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ;
    ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn
20 Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára
    sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó bá ọ jà
ṣùgbọ́n, wọn kò ní lè borí rẹ
    nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là,
kí n sì dáàbò bò ọ́,”
    ni Olúwa wí.
21 “Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn
    ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́
    padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”