Add parallel Print Page Options

Wọ́n fi ikú halẹ̀ mọ́ Jeremiah

26 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìjọba ọba Jehoiakimu ọmọ Josiah tí ń ṣe ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa: “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Dúró ní àgbàlá ilé Olúwa, kí o sì sọ fún gbogbo ènìyàn ilẹ̀ Juda tí ó ti wá láti wá jọ́sìn ní ilé Olúwa: sọ gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ; má ṣaláìsọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà. Bóyá gbogbo wọn máa gbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn yóò kúrò nínú ìwà búburú wọn. Èmi ó yí ọkàn padà, n kò sì ní fi ibi tí mo ti rò sí wọn ṣe wọ́n. Sọ fún wọn wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Tí ẹ kò bá fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò sì gbọ́ òfin mi, ti mo gbé kalẹ̀ níwájú yín, àti tí ẹ kò bá gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì tí mo rán sí i yín léraléra (ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́), nígbà náà ni èmi yóò ṣe ilé yìí bí Ṣilo, èmi yóò sì ṣe ìlú yìí ní ìfibú sí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.’ ”

Àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo ènìyàn ni ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Jeremiah tí ó sọ ní ilé Olúwa. Ṣùgbọ́n ní kété tí Jeremiah ti parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí Olúwa pàṣẹ láti sọ; àwọn àlùfáà, àti gbogbo ènìyàn dìímú, wọ́n sì wí pé, “Kíkú ni ìwọ yóò kú! Kí ló dé tí ìwọ ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa pé, ilé yìí yóò dàbí Ṣilo, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro tí kì yóò ní olùgbé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì kójọpọ̀ pẹ̀lú Jeremiah nínú ilé Olúwa.

10 Nígbà tí àwọn aláṣẹ Juda gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, wọ́n lọ láti ààfin ọba sí ilé Olúwa, wọ́n sì mú ààyè wọn, wọ́n jókòó ní ẹnu-ọ̀nà tuntun ilé Olúwa. 11 Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sọ fún àwọn aláṣẹ àti gbogbo ènìyàn pé, “Arákùnrin yìí gbọdọ̀ gba ìdájọ́ ikú nítorí pé ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórí ìlú yìí: bí ẹ̀yin ti fi etí yín gbọ́!”

12 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún gbogbo àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn wí pé: “Olúwa rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé yìí àti ìlú yìí, gbogbo ohun tí ẹ ti gbọ́. 13 Nísinsin yìí, tún ọ̀nà rẹ ṣe àti ìṣe rẹ, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. Olúwa yóò yí ọkàn rẹ̀ padà, kò sì ní mú ohun gbogbo tí ó ti sọ jáde ní búburú ṣẹ lórí yín. 14 Bí ó bá ṣe tèmi ni, èmi wà ní ọwọ́ yín, ẹ ṣe ohun tí ẹ̀yin bá rò pé ó dára, tí ó sì tọ́ lójú yín fún mi. 15 Ẹ mọ̀ dájú pé tí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín, sórí ìlú yìí àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; nítorí pé nítòótọ́ ni Olúwa ti rán mi láti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún un yín.”

16 Nígbà náà ni àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé, “Ẹ má ṣe pa ọkùnrin yìí nítorí ó ti bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.”

17 Lára àwọn àgbàgbà ilẹ̀ náà sì sún síwájú, wọ́n sì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, 18 “Mika ti Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Ó sọ fún gbogbo ènìyàn Juda pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“ ‘A ó sì fa Sioni tu bí oko
    Jerusalẹmu yóò di òkìtì
àlàpà àti òkè ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí
    ibi gíga igbó.’

19 Ǹjẹ́ Hesekiah ọba Juda tàbí ẹnikẹ́ni ní Juda pa á bí? Ǹjẹ́ Hesekiah kò bẹ̀rù Olúwa tí ó sì wá ojúrere rẹ̀? Ǹjẹ́ Olúwa kò ha a sì yí ìpinnu rẹ̀ padà, tí kò sì mú ibi tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ yẹ̀ kúrò lórí wọn? Ibi ni a fẹ́ mú wá sórí ara wa yìí.”

20 (Bákan náà Uriah ọmọ Ṣemaiah láti Kiriati-Jearimu jẹ́ ọkùnrin mìíràn tí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà ní orúkọ Olúwa. Ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà sí ìlú náà àti ilẹ̀ yín bí Jeremiah ti ṣe. 21 Nígbà tí ọba Jehoiakimu àti gbogbo àwọn aláṣẹ gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba ń wá láti pa á: ṣùgbọ́n Uriah gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí Ejibiti. 22 Ọba Jehoiakimu rán Elnatani ọmọ Akbori lọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mìíràn. 23 Wọ́n sì mú Uriah láti Ejibiti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Jehoiakimu; ẹni tí ó fi idà pa, ó sì sọ òkú rẹ̀ sí inú isà òkú àwọn ènìyàn lásán.)

24 Ahikamu ọmọ Ṣafani ń bẹ pẹ̀lú Jeremiah, wọn kò sì fi í lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti pa á.

Jeremiah Threatened With Death

26 Early in the reign of Jehoiakim(A) son of Josiah king of Judah, this word came from the Lord: “This is what the Lord says: Stand in the courtyard(B) of the Lord’s house and speak to all the people of the towns of Judah who come to worship in the house of the Lord.(C) Tell(D) them everything I command you; do not omit(E) a word. Perhaps they will listen and each will turn(F) from their evil ways. Then I will relent(G) and not inflict on them the disaster I was planning because of the evil they have done. Say to them, ‘This is what the Lord says: If you do not listen(H) to me and follow my law,(I) which I have set before you, and if you do not listen to the words of my servants the prophets, whom I have sent to you again and again (though you have not listened(J)), then I will make this house like Shiloh(K) and this city a curse[a](L) among all the nations of the earth.’”

The priests, the prophets and all the people heard Jeremiah speak these words in the house of the Lord. But as soon as Jeremiah finished telling all the people everything the Lord had commanded(M) him to say, the priests, the prophets and all the people seized(N) him and said, “You must die!(O) Why do you prophesy in the Lord’s name that this house will be like Shiloh and this city will be desolate and deserted?”(P) And all the people crowded(Q) around Jeremiah in the house of the Lord.

10 When the officials(R) of Judah heard about these things, they went up from the royal palace to the house of the Lord and took their places at the entrance of the New Gate(S) of the Lord’s house. 11 Then the priests and the prophets said to the officials and all the people, “This man should be sentenced to death(T) because he has prophesied against this city. You have heard it with your own ears!”(U)

12 Then Jeremiah said to all the officials(V) and all the people: “The Lord sent me to prophesy(W) against this house and this city all the things you have heard.(X) 13 Now reform(Y) your ways and your actions and obey(Z) the Lord your God. Then the Lord will relent(AA) and not bring the disaster he has pronounced against you. 14 As for me, I am in your hands;(AB) do with me whatever you think is good and right. 15 Be assured, however, that if you put me to death, you will bring the guilt of innocent blood(AC) on yourselves and on this city and on those who live in it, for in truth the Lord has sent me to you to speak all these words(AD) in your hearing.”

16 Then the officials(AE) and all the people said to the priests and the prophets, “This man should not be sentenced to death!(AF) He has spoken to us in the name of the Lord our God.”

17 Some of the elders of the land stepped forward and said to the entire assembly of people, 18 “Micah(AG) of Moresheth prophesied in the days of Hezekiah king of Judah. He told all the people of Judah, ‘This is what the Lord Almighty says:

“‘Zion(AH) will be plowed like a field,
    Jerusalem will become a heap of rubble,(AI)
    the temple hill(AJ) a mound overgrown with thickets.’[b](AK)

19 “Did Hezekiah king of Judah or anyone else in Judah put him to death? Did not Hezekiah(AL) fear the Lord and seek(AM) his favor? And did not the Lord relent,(AN) so that he did not bring the disaster(AO) he pronounced against them? We are about to bring a terrible disaster(AP) on ourselves!”

20 (Now Uriah son of Shemaiah from Kiriath Jearim(AQ) was another man who prophesied in the name of the Lord; he prophesied the same things against this city and this land as Jeremiah did. 21 When King Jehoiakim(AR) and all his officers and officials(AS) heard his words, the king was determined to put him to death.(AT) But Uriah heard of it and fled(AU) in fear to Egypt. 22 King Jehoiakim, however, sent Elnathan(AV) son of Akbor to Egypt, along with some other men. 23 They brought Uriah out of Egypt and took him to King Jehoiakim, who had him struck down with a sword(AW) and his body thrown into the burial place of the common people.)(AX)

24 Furthermore, Ahikam(AY) son of Shaphan supported Jeremiah, and so he was not handed over to the people to be put to death.

Footnotes

  1. Jeremiah 26:6 That is, its name will be used in cursing (see 29:22); or, others will see that it is cursed.
  2. Jeremiah 26:18 Micah 3:12